Kwara Hijab Crisis: Ẹ ṣe ohun tí àwọn Kristẹni Ilorin ń fẹ́ tàbí kí ẹ kó àwọn ọmọ yín kúrò nílé ẹ̀kọ́ wọn - Oyedepo
Oludasilẹ ijọ Living Faith ti ọpọ mọ si Winners, ti ke si awọn Musulumi niluu Ilorin lati ko awọn ọmọ wọn lọ sile ẹkọ awọn Musulumi ti wọn ba fẹ ki wọn maa lo ijaabu.
Oyedepo lo sọ ọrọ naa ninu iwaasu kan to ṣe lẹyin rogbodiyan ọrọ ijaabu to waye nile ẹkọ Baptist ati ECWA ni Ilorin.
Ṣaaju ni Gomina ipinlẹ Kwara, AbdulRahman AbdulRazaq, ti kọkọ paṣẹ pe awọn akẹkọọ to jẹ Musulumi le maa wọ ijaabu nile ẹkọ ti awọn ọmọlẹyin Kristi da silẹ.
- Àìgbọ́ra ẹni yé ẹ̀yà Yoruba ló ń ṣe ìdíwọ́ fún òmìnira wa - Àkójọpọ̀ ẹgbẹ́ Yoruba l'àgbáyé
- Ṣé òótọ́ ni pé Yusuf Buhari ń múra láti gbé Ọmọọbabìnrin Zahra Bayero níyàwó?
- Ṣé ǹkan ọmọkùnrín rẹ ò ní padà kéré báyìí? Wo tuntun tí onímọ̀ Sáyẹ̀nsì gbéjáde
- Wo ìdí tí Orílẹ́èdè Germany fi fẹ́ dá ère 530 ìlú Benin tí wọ́n jí padà sí Nàìjíríà
- Àlùwàlá ológbòò Tinubu pẹ̀lú ₦50m tó f'áwọn ará Katsina, ọgbọ́n àti kẹ́ran jẹ nínú ìbò 2023 ni
- Kí ló lè fàá kí Yomi Fabiyi àti PA rẹ̀ máa fẹnu ko ara wọn l'ẹ́nu?
Ṣugbọn aṣẹ naa ko dun mọ awọn Kristẹni ilu Ilorin ninu, eyii to da rogbodiyan silẹ.
Oyedepo ni "ohun to n ṣẹlẹ ni Kwara jẹ eyii to ba ni ninu jẹ gidi, nibi ti awọn awọn Musulumi ti sọ fun awọn Kristẹni lati gba ijaabu laaye nile ẹkọ ti wọn da silẹ"
"Mi o tii ri ibikibi laye yii ti ayalegbe yoo ti maa paṣẹ fun onile... eredi rẹ si ni pe a ko tii fi odikeji Ọlọrun han wọn."
Alufaa naa sọ pe o yẹ ki wọn kilọ fun awọn ẹlẹsin miran pe ki wọn ṣọra fun awọn Kristẹni, ki wọn ma baa ri ibinu Ọlọrun.
Oyedepo pari ọrọ rẹ pe ki awọn Musulumi ti ohun ti awọn Kristẹni n fẹ ko ba tẹ lọrun ko awọn ọmọ wọn lọ sile ẹkọ to jẹ ti awọn Musulumi.
"Ẹ dẹkun ati maa ki ika si oju ẹlomiran nigba ti wọn kii ṣe afọju," Oyedepo lo kilọ bẹẹ.
- Ayọ̀ abara tín-ín tín-ín! Wo àwọn òṣèré tó ti bímọ lọ́dún 2021 tí a wà yìí
- Christopher Sapara-Williams, ọmọ Ijesha tó di agbẹjọ́rò àkọ́kọ́ tó jẹ́ ọmọ Naijiria
- Ṣé lóòtọ́ ni pé Leah Sharibu bímọ ẹlẹ́ẹ̀kejì ní àhámọ́? Àlàyé rèé
- Iya Awero fẹ́rẹ̀ẹ́ bú sẹ́kún níbí tó ti tẹ́wọ́ gba ẹ̀bùn ilé tuntun
- Tinubu gbé ₦50m fún àwọn oníṣòwò tí ọjà wọn jóná ní Katsina
- Bí Kábíyèsì Ọba Tajudeen Omotayo ti Imope ṣe fara gbá mílíọ̀nù gọbọi kó tó bọ́ lọ́wọ́ ajínigbé - Ìdílé Alademeta
Ẹnikẹ́ni tó bá fa wàhálà míì lẹ́yìn rògbòdìyàn ọ̀rọ̀ Hijab tó wáyé n'Ilorin yóò fojú winá òfin - AbdulRazaq
Gomina ipinlẹ Kwara, AbdulRahman AbdulRazaq ti sọ pe ẹnikẹni to ba fa wahala nitori rogbodiyan ọrọ ijaabu to waye niluu Ilorin yoo foju wina ofin.
AbdulRazaq lo sọ ọrọ naa lasiko to n ba awọn eeyan ipinlẹ naa sọrọ lọjọ Isẹgun lẹyin rogbodiyan to waye ṣaju nile ẹkọ Batist ati ECWA niluu Ilorin.
Wahala ọhun bẹ silẹ lẹyin ti gomina ọhun kede lọjọ kẹrindinlọgbọn, oṣu Keji, ọdun yii pe, awọn akẹkọbinrin to jẹ Musulumi le maa wọ ijaabu lọ sile ẹkọ ti awọn Kristẹni da silẹ.
- Sùkẹ̀! Ọ̀rọ̀ òṣèlú ni gbogbo ẹ tí Akeredolu ṣe tako ìdásílẹ̀ Oduduwa Nation - Banji Akintoye
- "Afòjúsùn ẹgbẹ́ òsèlú APC ni láti ṣèjọba Naijiria fún ọdún méjìlélọ́gbọ̀n"
- Èèyàn lẹ́tọ̀ọ́ láti náwó yàlàyòlò lábẹ́ òfin, ṣùgbọ́n ọ̀nà tí ìjọba lè gbà tojú bọ owó rẹ rèé
- Wo àwọn ọ̀rọ̀ tó ki pọ́pọ́ tí Lateef Adedimeji fi kọrin ọjọ́ ìbí 23 fún Adebimpe Oyebade "Onítèmi"
Igbesẹ naa ko dun mọ wọn adari ile ẹkọ Kristẹni ọhun ninu, eyii to da wahala silẹ.
O ni oun ti kọkọ ṣe ipade pẹlu awọn ti ọrọ naa kan ṣaaju ki oun to gbe igbẹsẹ ọhun.
AbdulRazaq tun sọ pe gẹgẹ bii gomina, oun ti bura lati daabo bo awọn eeyan ilu lọwọ wahala ki irufẹ wahala bẹẹ to bẹ silẹ.
- Ẹ̀yà Yorùbá ti fara ṣiṣẹ́ púpọ̀ fún Naijiria, nítorí nàá à kò le déèdé sọ pé a fẹ́ kúrò - Àgbààgbà Yorùbá
- Bí òkú ṣe máa ń bàjẹ́ ní Mọ́ṣúárì tẹ́ẹ ò bá san owó ìtọ́jú fáwọn olùtọ́jú òkú rèé
- A ò pe Sunday Igboho lọ́mọ alè Yorùbá o àmọ́, a ó jọ́ bèrè lọ́wọ́ Alálẹ̀ Ibadan àti gbogbo Yorùbá ni - Olubadan
- Mo gbàdúrà kí n má kábàmọ́ fífagilé ẹjọ́ pẹ̀lú àwọn tó jí àwọn ìbejì mi gbé nílé ẹjọ́ - Akeugbagold
O fikun pe oun yoo ṣe atunsẹ si igbimọ to n ri si ọrọ naa ti oun ti gbe kalẹ ṣaaju laarin ọjọ diẹ si asiko yii, ki ọrọ naa patapata.
Lẹyin naa lo dupẹ lọwọ awọn adari ẹsin Kristẹni ati Musulumi fun akitiyan wọn ki alaafia le jọba niluu Ilorin ati lọwọ awọn agbofinro naa fun ipa ti wọn sa lati pana rogbodiyan to bẹ silẹ ṣaaju.
Gomina naa pari ọrọ rẹ pe, ki awọn eeyan ipinlẹ Kwara gbiyanju lati fi imọ ṣokan fun itẹsiwaju ipinlẹ naa lai fi ti ẹya tabi ẹsin ṣe.
Akẹ́kọ̀ọ́ kò yọjú sílé ẹ̀kọ́ lẹ́yìn tí àwọn olùkọ́ padà sẹnu iṣẹ́ nílèèwẹ tí rògbòdìyàn Hijab ti wáyé n'Ilorin
Awọn olukọ lawọn ile ẹkọ ti ijọba ti pàṣẹ iwọle pada ni ipinlẹ Kwara lori ọrọ wahala lilo Hijab ti pa aṣẹ naa mọ.
Nile ẹkọ Baptisti to wa lagbegbe Surulere ti BBC Yoruba ṣabẹwo si, a ri awọn olukọ naa ti wọn ti n pada sẹnu isẹ wọn.
Ninu ifọrọwerọ pẹlu awọn olukọ ọhun, wọn ni awọn ko ni nnkan mii lati ṣe bi ko ṣe pe ki wọn tẹle aṣẹ ijoba to gba awọn ṣiṣe.
Wamuwamu ni awọn agbofinro wa ni ẹnu ọna abawọle ile ẹkọ Baptist naa, sugbon akẹkọọ meji pere la ri nigba ti a kan sibẹ.
Alakoso ile ẹkọ girama Baptist, arabinrin Bamikole Julianah Adedoyin ti a ba sọrọ ni awọn n reti ki awọn akẹkọ yọjú, paapaa awọn to fẹ kọ idanwo asekagba WAEC.
O fi kun pe oun ti gbe igbeṣe lati maa pe awọn obi awọn akọkọọ naa ki wọn ma baa padanu iforukọsilẹ idanwo WAEC ọhun.
Ko si wahala kankan nigba ti a de ibẹ sugbon awon alaṣẹ ile ẹkọ naa ni awọn eeyan kan ti ja ferese ọọfisi alakoso ile ẹkọ alakọbẹrẹ, ti wọn si ba awọn irinṣẹ kan jẹ.
Olùkọ́ tí kò bá yọjú sí kíláàsì láwọn iléẹ̀kọ́ tí ìjà tí ń wáyé rugi oyin - Ìjọba Kwara
Ijọba ipinlẹ Kwara ti pasẹ pe ki awọn ileẹkọ mẹwa to jẹ ti ẹlẹsin Kristẹni ti ija ti waye lori ọrọ lilo ibori bẹrẹ to ẹkọ kikọ lọgan.
Atẹjade kan ti alaga ajọ to n mojuto eto ẹkọ girama nipinlẹ Kwara, Tescom, Mallam Bello Abubakar fisita lo pasẹ bẹẹ fawọn ọga ile ẹkọ ati olukọ to wa lawọn ile ẹkọ mẹwẹẹwa naa.
Atẹjade naa ni igbesẹ pipada si kilaasi ni yoo mu ki eto ẹkọ kikọ bẹrẹ loju ẹsẹ, kawọn akẹkọjade to n mura idanwo WAEC le joko se idanwo naa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Bí ọlọ́pàá bá tó bẹ́ẹ̀, kó dá wa lọ́nà, Yoruba kìí ṣe ara Naijiria mọ́ - Sunday Igboho
- Ẹyọ kan lára agbára tí mo ní, ni mo lò láti mú Wakili - Gani Adams
- Òpùrọ́ ló pọ̀ nínú àwọn oníṣẹ̀ṣe, olóòtọ́ọ́ wọn ṣọ̀wọ́n - Olugbon
- Ẹ lo Amotekun, OPC, Fijilanté àti ọ̀dẹ ìbílẹ̀ fétò ààbò - Ọba Tejuosho
- N kò ní baba ìsàlẹ̀ nínú òṣèlú, Ọ́lọ́run nìkan ni mo bẹ̀rù - Seyi Makinde
- Wo ewu tó rọ̀ ma kí wọn sin ọba tó ṣètùtù nílànà ẹ̀sìn Krìsítẹ́nì àti Islam
Bello wa dunkoko pe olukọ ti ko ba yọju sibi isẹ lawọn ile ẹkọ naa loni ọjọ Ẹti rugi oyin, ti yoo si foju wina ofin ijọba nitori awọn ko ni faaye gba iwa aibọwọ fofin.
Bakan naa ni atẹjade ọhun tun fewe ọmọ mọ awọn eeyan ti ọrọ naa kan leti lati mase tapa sofin nitori ipade alaafia laarin wọn ati ijọba yoo tẹsiwaju.
Bello ni ijọba kabamọ nipa inira ti titi ilẹkun awọn ile ẹkọ naa mu bawọn akẹkọ pẹlu afikun pe ijọba gbe igbesẹ naa nitori ipese alaafia ni.
Krìstẹ́nì 15 ló farapa nínú làásìgbò Hijab Ilorin, àwọn kan tún ṣiṣẹ́ abẹ - CAN
Ẹgbẹ awọn ọmọlẹyin Kristi (CAN) ni ipinlẹ Kwara ti sọ pe bii eeyan marundinlogun lo ṣeṣe lasiko rogbodiyan to waye niluu Ilorin laarin awọn Kristẹni ati Musulumi.
Akọwe ẹgbẹ naa nipinlẹ ọhun, alufaa Reuben Idowu Ibitoye, lo sọ ọrọ naa ninu ifọrọwerọ kan pẹlu BBC Yoruba.
Rogbodiyan naa ko ṣẹyin ọrọ ti ijọba ipinlẹ naa sọ pe awọn akẹkọọbinrin to jẹ Musulumi le maa lo ijaabu lawọn ile ẹkọ ti ile ijọsin da silẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Òpùrọ́ ló pọ̀ nínú àwọn oníṣẹ̀ṣe, olóòtọ́ọ́ wọn ṣọ̀wọ́n - Olugbon
- N kò ní baba ìsàlẹ̀ nínú òṣèlú, Ọ́lọ́run nìkan ni mo bẹ̀rù - Seyi Makinde
- A ń lọ ṣí ẹnu bodè Yorùbá tíjọba tìpa sílẹ̀, kí oúnjẹ wọlé nírọ̀rùn - Sunday Igboho
- Ẹyọ kan lára agbára tí mo ní, ni mo lò láti mú Wakili - Gani Adams
- A kọ òrìṣà babańlá wa sílẹ̀ ló jẹ́ kí ọ̀daràn darandaran máa pa wá bí ẹ̀fọn - Àwọn Oníṣẹ̀ṣe
- Ìtàn ayé John Magufuli, Ààrẹ Tanzania tọ́pọ̀ èèyàn ń pè ní 'bulldozer'
- Wo ohun tí o kò mọ̀ nípa Ààrẹ Tanzania, John Magufuli tó jáde láyé
- Wo ewu tó rọ̀ ma kí wọn sin ọba tó ṣètùtù nílànà ẹ̀sìn Krìsítẹ́nì àti Islam
Ibitoye ni "awọn eeyan to ṣeṣe lọjọru ti isẹlẹ naa waye le ni marundinlogun, koda wọn ṣiṣẹ abẹ fun awọn miran ninu wọn.
Lonii ẹwẹ, wọn tun ṣakọlu si awọn miran lagbegbe ECWA, ti wọn si kan awọn eeyan naa lapa ati ni ẹsẹ."
Alufaa naa fikun pe, awọn gẹgẹ bii Kristẹni ko ni ija kankan pẹlu awọn Musulumi, ijọba ipinlẹ Kwara ni awọn ba ni ọrọ.
O pari ọrọ rẹ pe o yẹ ki ijọba ṣe ododo lori ọrọ naa, ki wọn ma si ṣe ojuṣaaju ninu idajọ wọn.
Ofin Naijiria fi aye gba ẹnikọọkan lati mura nilana ẹsin rẹ - Abdulhameed
Nigba to n da si ọrọ naa, Ọjọgbọn O.Y Abdulhameed, to jẹ akọwe awọn ọmọ bibi ilu Ilorin ati ọjọgbọn ni Fasiti Ilorin sọ pe, o yẹ ki gbogbo eeyan niluu Ilorin bọwọ fun ohun ti ofin sọ.
O ni "orilẹ-ede to ni ofin ni Naijiria jẹ nitori naa o yẹ ki gbogbo awọn ti ọrọ yii kan tẹle ohun ti ofin sọ."
Gẹgẹ bo ṣe sọ, "ofin Naijiria, ori ọgbọn, ẹsẹ ikẹjọ fi aye fun gbogbo ọmọ Naijiria lati darapọ mọ ẹsin to ba wu wọn, bakan naa lo tun fi aye gba wọn lati mura bi ẹsin naa ṣe fi aye gba wọn."
Ọjọgbọn naa sọ fun BBC Yoruba pe, eeyan le mura bi ẹsin rẹ ṣe fi aye gba ni gbogbo ibi to ba jẹ ti ijọba, ti ile ẹkọ naa jẹ ọkan lara rẹ."
Akọwe ọmọ ilu Ilorin ṣalaye siwaju si pe, lootọ awọn ile ijọsin lo da awọn ile ẹkọ naa silẹ, ṣugbọn ijọba ti gba iṣakoso awọn ile ẹkọ ọhun lọwọ awọn ile ijọsin lọdun 1974.
O ni ti to ba jẹ pe ijọba lo n ṣagbatẹru awọn ile ẹkọ naa, ijọba nikan lo ni aṣẹ lati sọ bi awọn akẹkọọ ṣe le maa mura lọ sile iwe.
Lẹyin naa lo gba awọn eeyan ilu Ilorin nimọran lati fi suuru yanju ọrọ naa, ati pe ki wọn ma gba ọrọ ẹsin laaye lati ba ibagbepọ wọn jẹ.
Awa ko ri ẹnikẹni ti wọn fọ lori tabi to farapa - Ọlọpaa
BBC tun kan si agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Kwara, Ajayi Okasanmi Jeffery, to sọ pe awọn ko fi panpẹ ofin mu ẹnikẹni ninu awọn to da rogbodiyan silẹ niluu Ilorin.
Bo tilẹ jẹ pe o ni lootọ ni awọn gbọ pe awọn eeyan kan farapa nitori iṣẹlẹ to waye niwaju ile ẹkọ Baptist to wa ni Surulere, ṣugbọn awọn ko le fidi rẹ mulẹ pe ẹnikẹni farapa.
O sọ pe "a gbọ pe wọn fọ awọn kan lori, ṣugbọn awa ko ri ẹnikẹni ti wọn fọ lori tabi to farapa."
Jeffery pari ọrọ rẹ pe awọn ti bẹrẹ iṣẹ lati pana rogbodiyan to n waye niluu Ilorin nitori ọrọ ijaabu ọhun.
Ilorin dàrú lórí àṣẹ káwọn akẹ́kọ̀ọ́ Musulumi má a lo ìbòrí nílé ẹ̀kọ́ Krìsìtẹ́nì
Ọrọ ti di boolọ o yago fun mi ni ilu Ilọrin laarin awọn Musulumi ati Kristiẹni.
Rogbodiyan naa ko ṣẹyin ọrọ lilo ijaabu fun awọn akẹkọọbinrin to jẹ Musulumi, to n kawe nile ẹkọ ti awọn Kristẹni kọ.
Aarọ Ọjọru ni awọn Kristẹni bẹrẹ ifẹhonuhan lodi si igbeṣẹ ijọba ipinlẹ ọhun, eyi to faaye gba awọn akẹkọọbirin Musulumi lati maa lo ijaabu nile ẹkọ awọn Kristẹni.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ilé ẹ̀kọ́ 10 tíjọba Kwara tìpa di ṣíṣí padà, akẹ́kọ̀ọ́bìnrin le lo Hijab níbẹ̀
- Boko Haram gboró, ó dáná ṣun ìbùdó ológun, iléẹ̀kọ́ àti ilé ìwòsàn
- Agbébọn pa èèyàn 58 tó ń ti ọjà bọ̀, jó ọ̀pọ̀ ọkọ̀, fi oúnjẹ ṣòfò
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ afurasí márùn ún míràn lórí ikú ọmọ Fasoranti
- Wakili àtàwọn méjì míì dèrò ẹ̀wọ̀n lẹ́yìn tí wọ́n fẹ̀sùn ìpànìyàn, ìjínigbé àti olè kàn wọ́n
- Àwọn agbébọn jí èèyàn méjì gbé ní ibùdó tí wọ́n tí ń fọ́ òkúta ní Ibadan
- Agbẹnusọ Sunday Igboho ná N2.5m bíí owó oúnjẹ́ lásán, gbas gbos bẹ̀rẹ̀
- "Torí ₦20, ọlọ́pàá yìnbọn fún mi lọ́rùn, n kò sì le b'óbìnrin lòpọ̀ mọ́ tàbí bímọ''
- Bí Buhari kò bá ṣọ́ra, àwọn ọba alayé ni yóò ṣaájú ìjìjàgbara fún Yorùbá - Sunday Igboho
- Èèyàn mẹ̀rin kú, 189 wà nílé ìwòsàn torí ayédèrú ohun mímu tí wọn mu
Igbesẹ naa ko dun mọ awọn alaṣẹ ile ẹkọ Kristẹni naa ninu, lẹyin ti wọn ti kọkọ sọ ṣaaju pe akẹkọọ yowu to ba fẹ maa kawe nile iwe awọn ko gbọdọ wọ ijaabu.
Lowurọ Ọjọru ni awọn ẹlẹsin mejeeji peju siwaju ileewe Baptist Secondary School to wa ni Suurulere, pẹlu iwe ilewọ to ni oriṣiriṣi akọle.
Ka to diju ki a to laa, ija ti bẹrẹ laarin awọn ẹlẹsin mejeji ọhun, ti ọlọpaa si yin afẹfẹ tajutaju soke lati tu wọn ka.
Awọn Musulumi ati Kristẹni bẹrẹ si n sọ oko sira wọn, eyii to mu awọn agbofinro yin gaasi tajutaju lọna ati pana rogbodiyan ọhun.
Titi di asiko ti a n kọ iroyin yii, awọn kristeni ti sa wọ inu ọgba sọọsi onitẹbọmi kan ni Suurulere, ti awọn Musulumi ṣi wa nita nibẹ.
Ti ẹ ko ba gbagbe, ọjọ Iṣẹgun ni ijọba ipinlẹ Kwara kede ṣiṣi awọn ile ẹkọ mẹwaa kan ti ọrọ naa kan pada, eyi ti wọn gbe ti pa ṣaaju.